27
Ìdáǹdè Israẹli
1 Ní ọjọ́ náà,
idà rẹ̀ a mú bí iná tí ó tóbi tí ó sì lágbára
Lefitani ejò tí ń yọ̀ tẹ̀ẹ̀rẹ̀ n nì,
Lefitani ejò tí ń lọ́ bìrìkìtì;
Òun yóò sì pa ẹ̀mí búburú inú Òkun náà.
2 Ní ọjọ́ náà,
“Kọrin nípa ọgbà àjàrà eléso kan.
3 Èmi Olúwa ń bojútó o,
Èmi ó bomirin ín láti ìgbàdégbà.
Èmi ó ṣọ́ ọ tọ̀sán tòru
kí ẹnikẹ́ni má ba à pa á lára.
4 Inú kò bí mi.
Bí ẹ̀gún àti ẹ̀wọ̀n bá dojú ìjà kọ mí!
Èmi yóò dìde sí wọn ní ogun,
Èmi yóò sì dáná sun gbogbo wọn.
5 Bí bẹ́ẹ̀ kọ́, jẹ́ kí wọn wá sọ́dọ̀ mi fún ààbò;
jẹ́ kí wọ́n wá àlàáfíà pẹ̀lú mi,
bẹ́ẹ̀ ni, jẹ́ kí wọn wá àlàáfíà pẹ̀lú mi.”
6 Ní ọjọ́ iwájú Jakọbu yóò ta gbòǹgbò,
Israẹli yóò tanná yóò sì rudi
èso rẹ̀ yóò sì kún gbogbo ayé.
7 Ǹjẹ́ Olúwa ti lù ú
gẹ́gẹ́ bí ó ti lu àwọn tí ó lù ú bolẹ̀?
Ǹjẹ́ a ti pa á
gẹ́gẹ́ bí a ti pa àwọn tí ó pa á?
8 Nípa ogun jíjà àti ìjìyà ti o le ni ó
fi dojúkọ ọ́
pẹ̀lú ìjì gbígbóná ni ó lé e jáde,
gẹ́gẹ́ bí ọjọ́ tí afẹ́fẹ́ ìlà-oòrùn fẹ́.
9 Nítorí èyí báyìí ni ètùtù yóò ṣe wà
fún ẹ̀ṣẹ̀ Jakọbu,
èyí ni yóò sì jẹ́ èso kíkún ti
ìmúkúrò ẹ̀ṣẹ̀ rẹ.
Nígbà tí ó bá mú kí àwọn òkúta pẹpẹ
dàbí òkúta ẹfun tí a fọ́ sí wẹ́wẹ́,
kì yóò sí ère Aṣerah tàbí pẹpẹ tùràrí
tí yóò wà ní ìdúró.
10 Ìlú olódi náà ti dahoro,
ibùdó ìkọ̀sílẹ̀, tí a kọ̀ tì
gẹ́gẹ́ bí aginjù;
níbẹ̀ ni àwọn ọmọ màlúù ti ń jẹ oko
níbẹ̀ ni wọn ń sùn sílẹ̀;
wọn sì jẹ gbogbo ẹ̀ka rẹ̀ tán.
11 Nígbà tí àwọn ẹ̀ka rẹ̀ bá rọ, a ó ya wọn dànù
àwọn obìnrin dé, wọ́n sì fi wọ́n dáná
nítorí aláìlóye ènìyàn ni wọn jẹ́,
nítorí náà ni ẹni tí ó dá wọn kì yóò ṣàánú fún wọn;
bẹ́ẹ̀ ni ẹni tí ó mọ wọn kì yóò sì fi ojúrere wò wọ́n.
12 Ní ọjọ́ náà
27:13 Mt 24.31; 1Kọ 15.52; 1Tẹ 4.16.